ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w98 1/1 ojú ìwé 29
  • “Sọ Àwọn Ènìyàn Gbogbo Orílẹ̀-Èdè Di Ọmọ Ẹ̀yìn”

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • “Sọ Àwọn Ènìyàn Gbogbo Orílẹ̀-Èdè Di Ọmọ Ẹ̀yìn”
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1998
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1998
w98 1/1 ojú ìwé 29

“Sọ Àwọn Ènìyàn Gbogbo Orílẹ̀-Èdè Di Ọmọ Ẹ̀yìn”

“NÍTORÍ náà ẹ lọ kí ẹ sì máa sọ àwọn ènìyàn gbogbo orílẹ̀-èdè di ọmọ ẹ̀yìn, ẹ máa batisí wọn ní orúkọ Baba àti ti Ọmọkùnrin àti ti ẹ̀mí mímọ́.” Bí Ìtumọ̀ Ayé Titun ṣe tú àṣẹ Jésù tí ó wà nínú Mátíù 28:19 nìyí. Ṣùgbọ́n, a ti ṣe lámèyítọ́ ọ̀nà tí a gbà tú u yìí. Fún àpẹẹrẹ, ìwé ìléwọ́ kékeré ti ìsìn kan sọ pé: “Ìtumọ̀ kan ṣoṣo tí ẹsẹ Gíríìkì náà fàyè gbà ni: ‘Sọ gbogbo orílẹ̀-èdè di ọmọ ẹ̀yìn!’” Òtítọ́ ha ni èyí bí?

Ìtumọ̀ yí, “Sọ gbogbo orílẹ̀-èdè di ọmọ ẹ̀yìn,” fara hàn nínú ọ̀pọ̀ ìtumọ̀ Bíbélì, ó sì jẹ́ títú èdè Gíríìkì lọ́nà ṣangiliti. Nítorí náà, ìdí wo ni ó wà fún títú u sí, “Sọ àwọn ènìyàn gbogbo orílẹ̀-èdè di ọmọ ẹ̀yìn, ẹ máa batisí wọn”? Àyíká ọ̀rọ̀ rẹ̀ ni. Gbólóhùn ọ̀rọ̀ náà, “ẹ máa batisí wọn” tọ́ka sí àwọn ènìyàn ní kedere, kì í ṣe sí àwọn orílẹ̀-èdè. Ọ̀mọ̀wé akẹ́kọ̀ọ́jinlẹ̀ ara Germany náà, Hans Bruns, sọ pé: “[Ọ̀rọ̀] náà, ‘wọn’ kò tọ́ka sí àwọn orílẹ̀-èdè (ọ̀rọ̀ Gíríìkì náà fi ìyàtọ̀ hàn kedere), bí kò ṣe sí àwọn ènìyàn tí ó wà ní àwọn orílẹ̀-èdè.”

Síwájú sí i, ó yẹ kí a gbé ọ̀nà tí a gbá mú àṣẹ Jésù ṣẹ yẹ̀ wò. Nípa iṣẹ́ òjíṣẹ́ Pọ́ọ̀lù àti Bánábà ní Déébè, ìlú kan ní Éṣíà Kékeré, a kà pé: “Lẹ́yìn pípolongo ìhìn rere fún ìlú ńlá yẹn àti sísọ àwọn púpọ̀ díẹ̀ di ọmọ ẹ̀yìn, wọ́n pa dà sí Lísírà àti Íkóníónì àti sí Áńtíókù.” (Ìṣe 14:21) Kíyè sí i pé kì í ṣe ìlú Déébè ni Pọ́ọ̀lù àti Bánábà sọ di ọmọ ẹ̀yìn, bí kò ṣe díẹ̀ lára àwọn ènìyàn Déébè.

Bákan náà, ní ti ọjọ́ ìkẹyìn, ìwé Ìṣípayá kò sọ tẹ́lẹ̀ pé gbogbo orílẹ̀-èdè yóò wá sin Ọlọ́run, ṣùgbọ́n pé “ogunlọ́gọ̀ ńlá kan . . . láti inú gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè àti ẹ̀yà àti ènìyàn àti ahọ́n” ni yóò ṣe bẹ́ẹ̀. (Ìṣípayá 7:9) Nípa báyìí, Ìtumọ̀ Ayé Titun fi hàn gbangba pé òun jẹ́ ìtumọ̀ tí ó ṣeé gbára lé ti ‘gbogbo Ìwé Mímọ́, tí Ọlọ́run mí sí.’—Tímótì Kejì 3:16.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́