ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w98 7/1 ojú ìwé 7
  • Kíkẹ́kọ̀ọ́ Láti Inú Àṣìṣe Àtẹ̀yìnwá

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Kíkẹ́kọ̀ọ́ Láti Inú Àṣìṣe Àtẹ̀yìnwá
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1998
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìbéèrè Láti Ọwọ́ Àwọn Òǹkàwé
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2005
  • Ìjẹ́wọ́ Tí Ń Yọrí sí Ìwòsàn
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2001
  • Àánú Jehofa Ń Gbà Wá Là Kuro Ninu Ainireti
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1993
  • O Lè Máa Bá Híhùwà Mímọ́ Nìṣó
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2000
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1998
w98 7/1 ojú ìwé 7

Kíkẹ́kọ̀ọ́ Láti Inú Àṣìṣe Àtẹ̀yìnwá

ÒFIN Ẹlẹ́dàá wa lórí ìwà híhù wà títí ayérayé, kì í sì í yí padà. Nítorí ìdí yìí, ìlànà tí a rí nínú Gálátíà 6:7 kàn wá lónìí: “Ohun yòówù tí ènìyàn bá ń fúnrúgbìn, èyí ni yóò ká pẹ̀lú.” Lóòótọ́, ẹnì kan lè sọ pé òun kò ní jíhìn fún Ọlọ́run, ṣùgbọ́n ìlànà àtọ̀runwá kò ṣeé yí padà. Ní àsẹ̀yìnwá-àsẹ̀yìnbọ̀, kò sí ẹnì kan tí kò ní jíhìn fún àwọn ìgbésẹ̀ rẹ̀.

Ẹnì kan tí ó gbé ìgbésí ayé oníwà wíwọ́, tí ó yí padà, tí ó sì di ìránṣẹ́ Ọlọ́run ńkọ́? Ó ṣì lè ní láti kojú àwọn àbájáde ìgbésí ayé rẹ̀ àtijọ́. Àmọ́ ṣá o, èyí kò túmọ̀ sí pé Ọlọ́run kò tí ì dárí jì í. Panṣágà tí Dáfídì Ọba ṣe pẹ̀lú Bátí-ṣébà mú ìjàǹbá wá sínú ìgbésí ayé rẹ̀. Kò lè yẹ̀ ẹ́ sílẹ̀. Ṣùgbọ́n ó ronú pìwà dà, ó sì rí ìdáríjì Ọlọ́run gbà.—2 Sámúẹ́lì 12:13-19; 13:1-31.

Ọkàn rẹ ha ń bà jẹ́ nígbà tí o bá jìyà àbájáde àṣìṣe tí o ti ṣe sẹ́yìn bí? Bí o bá fojú tí ó tọ́ wò ó, kíkábàámọ̀ lè rán wa létí láti ‘ṣọ́ra kí a má ṣe yíjú sí ohun tí ń ṣeni lọ́ṣẹ́.’ (Jóòbù 36:21) Bẹ́ẹ̀ ni, kíkábàámọ̀ lè ràn wá lọ́wọ́ láti yẹra fún ṣíṣe àṣìṣe kan náà léraléra. Èyí tí ó tún dára jù ni pé, Dáfídì kò lo ìrírí tí ó ní nínú ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ṣẹ̀ láti ṣe ara rẹ̀ nìkan láǹfààní ṣùgbọ́n ó lò ó láti ṣe àwọn ẹlòmíràn láǹfààní pẹ̀lú. Ó wí pé: “Èmi yóò kọ́ àwọn olùrélànàkọjá ní àwọn ọ̀nà rẹ, kí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ pàápàá lè yí padà tààràtà sọ́dọ̀ rẹ.”—Sáàmù 51:13.

[Àwọn àwòrán tó wà ní ojú ìwé 7]

Dáfídì kẹ́kọ̀ọ́ láti inú ẹ̀ṣẹ̀ tí ó dá pẹ̀lú Bátí-ṣébà

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́