January 7-13
ÌṢE 21-22
- Orin 55 àti Àdúrà 
- Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) 
ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN
- “Kí Ìfẹ́ Jèhófà Ṣẹ”: (10 min.) - Iṣe 21:8-12—Àwọn Kristẹni kan ń rọ Pọ́ọ̀lù pé kó má ṣe lọ sí Jerúsálẹ́mù torí ewu tó ń dúró dè é níbẹ̀ (bt 177-178 ¶15-16) 
- Iṣe 21:13—Pọ́ọ̀lù pinnu pé ìfẹ́ Jèhófà lòun máa ṣe (bt 178 ¶17) 
- Iṣe 21:14—Nígbà tí àwọn ará rí i pé Pọ́ọ̀lù ò yí ìpinnu rẹ̀ pa dà, wọ́n fara mọ́ ìpinnu tó ṣe (bt 178 ¶18) 
 
- Máa Walẹ̀ Jìn Nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: (8 min.) - Iṣe 21:23, 24—Tó bá jẹ́ pé lóòótọ́ làwọn Kristẹni ò sí lábẹ́ Òfin Mósè mọ́, kí nìdí tí àwọn alàgbà tó wà ní Jerúsálẹ́mù fi fún Pọ́ọ̀lù ní ìtọ́ni yìí? (bt 184-185 ¶10-12) 
- Iṣe 22:16—Báwo ni Pọ́ọ̀lù ṣe lè wẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ nù? (“wẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nù nípa kíké tí o bá ń ké pe orúkọ rẹ̀” àlàyé ọ̀rọ̀ lórí Iṣe 22:16, nwtsty) 
- Kí ni Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí kọ́ ẹ nípa Jèhófà? 
- Àwọn ìṣúra tẹ̀mí wo lo tún rí látinú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí? 
 
- Bíbélì Kíkà: (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Iṣe 21:1-19 (th ẹ̀kọ́ 5)a 
MÁA LO ARA RẸ LẸ́NU IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ
- Tẹra Mọ́ Kíkàwé àti Kíkọ́ni: (10 min.) Ìjíròrò. Ẹ wo fídíò Ìnasẹ̀ Ọ̀rọ̀ Tó Dára, lẹ́yìn náà, ẹ jíròrò ẹ̀kọ́ 1 nínú ìwé pẹlẹbẹ Kíkọ́ni. 
- Àsọyé: (5 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) w10 2/1 13 ¶2–14 ¶2—Àkòrí: Ǹjẹ́ Ó Pọn Dandan Káwọn Kristẹni Máa Pa Sábáàtì Mọ́? (th ẹ̀kọ́ 1)b 
MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
- “Jèhófà Ló Bá Wa Tọ́ Àwọn Ọmọ Wa”: (15 min.) Ìjíròrò. Jẹ́ kí àwọn ará wo fídíò náà. 
- Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ: (30 min.) bh orí 1 ¶14-17 àti Àfikún Ìtumọ̀ Orúkọ Ọlọ́run àti Ìdí Tó Fi Yẹ Ká Máa Lò Ó 
- Àtúnyẹ̀wò àti Ohun Tá A Máa Kọ́ Lọ́sẹ̀ Tó Ń Bọ̀ (3 min.) 
- Orin 70 àti Àdúrà