MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
Máa Fọkàn Yàwòrán Ohun Tó Ò Ń Kà
Tó o bá ń ka Bíbélì, máa fọkàn yàwòrán ohun tó ò ń kà. Ronú nípa àyíká ọ̀rọ̀ yẹn, àwọn tá a mẹ́nu kàn àti ohun tó ṣeé ṣe kó fà á tí wọ́n fi ṣe ohun tí wọ́n ṣe. Fojú inú wò ó bíi pé o wà níbẹ̀, kí làwọn ohun tó o máa rí, kí ló ṣeé ṣe kó o gbọ́, báwo nibẹ̀ ṣe ń rùn, báwo sì ni nǹkan ṣe rí lára ẹni náà?
JẸ́ KÍ ÀWỌN ARÁ WO FÍDÍÒ NÁÀ MÚ KÍ BÓ O ṢE Ń KA BÍBÉLÌ SUNWỌ̀N SÍ I—ÀYỌLÒ, LẸ́YÌN NÁÀ, Ẹ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:
- Kí làwọn nǹkan tó ṣeé ṣe kó fà á tí àárín Jósẹ́fù àtàwọn ẹ̀gbọ́n ẹ̀ ò fi gún? 
- Kí ló ṣeé ṣe kó fà á táwọn ẹ̀gbọ́n Jósẹ́fù fi bínú ẹ̀ débi tí wọ́n fi hùwà láìronú ohun tó máa tẹ̀yìn ẹ̀ yọ? 
- Tá a bá ronú nípa ohun tí Bíbélì sọ nípa Jékọ́bù, kí la lè sọ nípa irú ẹni tó jẹ́? 
- Àpẹẹrẹ tó dáa wo ni Jékọ́bù fi lélẹ̀ fáwọn ọmọ ẹ̀ tó bá dọ̀rọ̀ ká yanjú aáwọ̀? 
- Ẹ̀kọ́ wo lo rí kọ́ nínú fídíò yìí?