ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb23 July ojú ìwé 15
  • Máa Fìfẹ́ Tí Kì Í Yẹ̀ Hàn Bíi Ti Jèhófà

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Máa Fìfẹ́ Tí Kì Í Yẹ̀ Hàn Bíi Ti Jèhófà
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2023
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Báwo Ni Ìfẹ́ Jèhófà Tí Kì Í Yẹ̀ Ṣe Ń Ṣe Ọ́ Láǹfààní?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2021
  • Ṣé Inú Rẹ Máa Ń Dùn sí Ìfẹ́ Tí Kì Í Yẹ̀ Bíi Ti Jèhófà?
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Àwa Kristẹni​—Ìwé Ìpàdé (2017)
  • Báwo La Ṣe Lè Fi Hàn Pé A Nífẹ̀ẹ́ Jèhófà?
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
  • Jèhófà Ní Ìfẹ́ Oníjẹ̀lẹ́ńkẹ́ Sí Ẹ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2024
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2023
mwb23 July ojú ìwé 15

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Máa Fìfẹ́ Tí Kì Í Yẹ̀ Hàn Bíi Ti Jèhófà

Jèhófà ló fi àpẹẹrẹ tó ga jù lọ lélẹ̀ tó bá dọ̀rọ̀ ká fìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn sẹ́nì kan. (Sm 103:11) Ìfẹ́ yìí kì í ṣe ìmọ̀lára kan lásán tó kàn wà fún ìgbà díẹ̀; àwọn tó bá ní ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ síra wọn máa ń sún mọ́ra pẹ́kípẹ́kí, ìfẹ́ yẹn máa ń jinlẹ̀ gan-an, ó sì máa ń wà pẹ́ títí. Onírúurú ọ̀nà ni Jèhófà gbà fi ìfẹ́ yìí hàn sáwọn ọmọ Ísírẹ́lì. Ó gbà wọ́n sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ará Íjíbítì tó ń fi wọ́n ṣẹrú, ó sì mú wọn wá sí Ilẹ̀ Ìlérí. (Sm 105:42-44) Ó máa ń jà fáwọn èèyàn rẹ̀, léraléra ló sì máa ń dárí jì wọ́n tí wọ́n bá ṣẹ̀. (Sm 107:19, 20) Bá a ṣe ń “fara balẹ̀ kíyè sí àwọn ohun tí Jèhófà ṣe nítorí ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀,” ó máa ń wù wá láti fara wé e.​—Sm 107:43.

Àwòrán: Àwọn àwòrán tó dá lórí fídíò “Fara Balẹ̀ Kíyè Sí Àwọn Ohun Tí Jèhófà Ṣe Nítorí Ìfẹ́ Rẹ̀ Tí Kì Í Yẹ̀.” 1. Arákùnrin Capra àti arákùnrin míì lọ bẹ arábìnrin kan wò nílé. 2. Arákùnrin Capra wà lẹ́wọ̀n pẹ̀lú àwọn arákùnrin míì, ó sì ń fún arákùnrin kan tára ẹ̀ ò yá tó sùn sórí bẹ́ẹ̀dì lóúnjẹ.

Ẹ WO FÍDÍÒ NÁÀ “FARA BALẸ̀ KÍYÈ SÍ ÀWỌN OHUN TÍ JÈHÓFÀ ṢE NÍTORÍ ÌFẸ́ RẸ̀ TÍ KÌ Í YẸ̀,” KẸ́ Ẹ SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Àwọn ọ̀nà wo la lè gbà fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn?

  • Kí nìdí tá a fi gbọ́dọ̀ yááfì àwọn nǹkan kan tá a bá fẹ́ fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́