MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
“Èmi Nìyí! Rán Mi!”
Aísáyà fi àpẹẹrẹ rere lélẹ̀ fún wa, torí pé ó múra tán láti jíṣẹ́ tí Ọlọ́run rán an. Ó fi hàn pé òun nígbàgbọ́, torí pé kíá ló yọ̀ǹda ara rẹ̀ láti lọ ṣe iṣẹ́ náà, bó tilẹ̀ jẹ́ pé kó mọ gbogbo ohun tó rọ̀ mọ́ ọn. (Ais 6:8) Ǹjẹ́ ìwọ náà lè ṣe àwọn àyípadà kan kó o lè lọ sìn níbi tá a ti nílò àwọn oníwàásù Ìjọba Ọlọ́run púpọ̀ sí i? (Sm 110:3) Àmọ́ kó o tó lọ, ó ṣe pàtàkì pé kó o “gbéṣirò lé ìnáwó náà.” (Lk 14:27, 28) Síbẹ̀, ó dáa kó o múra tán láti yááfì àwọn nǹkan kan nítorí iṣẹ́ ìwàásù. (Mt 8:20; Mk 10:28-30) Bá a ṣe rí i nínú fídíò tá a pé àkọlé rẹ̀ ní A Kó Lọ Síbi Tí Wọ́n Ti Nílò Oníwàásù Púpọ̀ Sí I, àwọn ìbùkún tí à ń rí gbà lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn Jèhófà kọjá ohunkóhun tá a lè yááfì.
LẸ́YÌN TÓ O BÁ TI WO FÍDÍÒ NÁÀ, DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:
- Àwọn nǹkan wo ni ìdílé Arákùnrin Williams yááfì kí wọ́n lè lọ sìn lórílẹ̀-èdè Ecuador? 
- Kí làwọn nǹkan tí wọ́n gbé yẹ̀wò kí wọ́n tó yan ibi tí wọ́n máa lọ? 
- Àwọn ìbùkún wo ni wọ́n rí gbà? 
- Ibo lo ti lè rí ìsọfúnni nípa lílọ sìn níbi tá a ti nílò àwọn oníwàásù púpọ̀ sí i? 
NÍGBÀ ÌJỌSÌN ÌDÍLÉ YÍN TÓ KÀN, Ẹ JÍRÒRÒ ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:
- Báwo la ṣe lè mú iṣẹ́ ìsìn wa gbòòrò sí i nínú ìdílé wa? (km 11/11 ojú ìwé 5 sí 7) 
- Tí a ò bá lè lọ sìn níbi tá a ti nílò àwọn oníwàásù púpọ̀ sí i, àwọn ọ̀nà míì wo la lè gbà ran ìjọ wa lọ́wọ́? (w16.03 ojú ìwé 3 sí 5)