ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • ijwyp àpilẹ̀kọ 110
  • Ṣé Kí N Ṣèrìbọmi?—Apá 2: Bó O Ṣe Lè Múra Sílẹ̀ fún Ìrìbọmi

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ṣé Kí N Ṣèrìbọmi?—Apá 2: Bó O Ṣe Lè Múra Sílẹ̀ fún Ìrìbọmi
  • Àwọn Ọ̀dọ́ Béèrè Pé
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Báwo ni nǹkan tí mo mọ̀ ṣe gbọ́dọ̀ pọ̀ tó?
  • Kí ló yẹ kí n máa ṣe?
  • Ẹ̀yin Ọ̀dọ́—Báwo Lẹ Ṣe Lè Múra Sílẹ̀ fún Ìrìbọmi?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2016
  • Ṣó Yẹ Kí N Ṣèrìbọmi?
    Àwọn Ìbéèrè Tí Àwọn Ọ̀dọ́ Ń Béèrè—Àwọn Ìdáhùn Tí Ó Gbéṣẹ́, Apá Kejì
  • Ṣé O Ti Ṣe Tán Láti Ṣèrìbọmi?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020
  • Ìrìbọmi Ṣe Pàtàkì!
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
Àwọn Míì
Àwọn Ọ̀dọ́ Béèrè Pé
ijwyp àpilẹ̀kọ 110
Obìnrin kan ń lo Bíbélì àtàwọn ìwé tó ṣàlàyé Bíbélì láti ṣèwádìí nípa ìrìbọmi.

ÀWỌN Ọ̀DỌ́ BÉÈRÈ PÉ

Ṣé Kí N Ṣèrìbọmi?​—Apá 2: Bó O Ṣe Lè Múra Sílẹ̀ fún Ìrìbọmi

Tó o bá ń tẹ̀ lé àwọn ìlànà Bíbélì, tó o sì ń ṣe àwọn nǹkan táá jẹ́ kó o túbọ̀ máa sún mọ́ Jèhófà, ó dájú pé wàá tí máa ronú nípa ṣíṣe ìrìbọmi. Àmọ́, báwo lo ṣe máa mọ̀ pé o ti ṣe tán láti ṣèrìbọmi?a

Nínú àpilẹ̀kọ yìí

  • Báwo ni nǹkan tí mo mọ̀ ṣe gbọ́dọ̀ pọ̀ tó?

  • Kí ló yẹ kí n máa ṣe?

  • Ohun táwọn ojúgbà ẹ sọ

Báwo ni nǹkan tí mo mọ̀ ṣe gbọ́dọ̀ pọ̀ tó?

Tó o bá ń múra láti ṣèrìbọmi, kò pọn dandan kó o máa há ohun tó ò ń kọ́ sórí bí ìgbà tó ò ń múra ìdánwò nílé ìwé. Àmọ́, o gbọ́dọ̀ lo “agbára ìrònú” rẹ kó lè túbọ̀ dá ẹ lójú pé òtítọ́ làwọn ẹ̀kọ́ tó ò ń kọ́ nínú Bíbélì. (Róòmù 12:1) Bí àpẹẹrẹ:

  • Ṣé ó dá ẹ lójú pé Ọlọ́run wà àti pé òun ló yẹ kó o máa sìn?

    Bíbélì sọ pé: “Ẹnikẹ́ni tó bá ń tọ Ọlọ́run wá gbọ́dọ̀ gbà gbọ́ pé ó wà àti pé òun ló ń san èrè fún àwọn tó ń wá a tọkàntọkàn.”​—Hébérù 11:6.

    Bi ara ẹ pé: ‘Kí ló mú kí n gba Ọlọ́run gbọ́?’ (Hébérù 3:4) ‘Kí nìdí tó fi jẹ́ pé òun ló yẹ kí n máa sìn?’​—Ìfihàn 4:11.

    Ohun tó lè ràn ẹ́ lọ́wọ́: Wo àpilẹ̀kọ náà “Ṣé Ẹ̀kọ́ Ẹfolúṣọ̀n Tọ̀nà àbí Ẹlẹ́dàá Kan Wà?​—Apá 1: Kí nìdí tó fi yẹ ká gbà pé Ọlọ́run wà?”

  • Ṣé ó dá ẹ lójú pé Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ló wà nínú Bíbélì lóòótọ́?

    Bíbélì sọ pé: “Gbogbo Ìwé Mímọ́ ni Ọlọ́run mí sí, ó sì wúlò fún kíkọ́ni, fún bíbáni wí, fún mímú nǹkan tọ́, fún títọ́nisọ́nà nínú òdodo”​—2 Tímótì 3:16.

    Bi ara ẹ pé: ‘Kí ló mú kí n gbà pé èrò èèyàn kọ́ ló wà nínú Bíbélì?’​—Àìsáyà 46:10; 1 Tẹsalóníkà 2:13.

    Ohun tó lè ràn ẹ́ lọ́wọ́: Wo àpilẹ̀kọ náà “Báwo Ni Bíbélì Ṣe Lè Ràn Mí Lọ́wọ́?​—Apá Kìíní: Wo Ohun Tó Wà Nínú Bíbélì.”

  • Ṣé ó dá ẹ lójú pé ìjọ Kristẹni ni Jèhófà ń lò láti mú ìfẹ́ rẹ̀ ṣẹ?

    Bíbélì sọ pé: “[Ọlọ́run] ni kí ògo jẹ́ tirẹ̀ nípasẹ̀ ìjọ àti nípasẹ̀ Kristi Jésù títí dé gbogbo ìran láé àti láéláé.”​—Éfésù 3:21.

    Bi ara ẹ pé: ‘Ṣé mo gbà pé ọ̀dọ̀ Jèhófà làwọn nǹkan tá à ń gbọ́ láwọn ìpàdé Kristẹni ti ń wá, kì í ṣe ọ̀dọ̀ èèyàn?’ (Mátíù 24:45) ‘Ṣé mo máa ń lọ sípàdé déédéé, kódà táwọn òbí mi ò bá lè lọ (tí wọ́n bá gbà ẹ́ láyè láti máa lọ)?’​—Hébérù 10:24, 25.

    Ohun tó lè ràn ẹ́ lọ́wọ́: Wo àpilẹ̀kọ náà “Kí Nìdí Tó Fi Yẹ Kí N Lọ sí Gbọ̀ngàn Ìjọba?”

Kí ló yẹ kí n máa ṣe?

Kò dìgbà tó o bá di ẹni tó pé kó o tó lè ṣèrìbọmi. Àmọ́, o gbọ́dọ̀ máa ṣe àwọn nǹkan tó fi hàn pé o fẹ́ “jáwọ́ nínú ohun búburú, kí o sì máa ṣe rere” (Sáàmù 34:14) Bí àpẹẹrẹ:

  • Ṣé o máa ń fi àwọn ìlànà Jèhófà sílò nígbèésì ayé rẹ?

    Bíbélì sọ pé: “Ẹ ní ẹ̀rí ọkàn rere”​—1 Pétérù 3:16.

    Bi ara ẹ pé: ‘Àwọn nǹkan wo ni mo ti ṣe tó fi hàn pé mo ti “kọ́ agbára ìfòyemọ̀” mi, kí n lè máa “fi ìyàtọ̀ sáàárín ohun tó tọ́ àti ohun tí kò tọ́”?’ (Hébérù 5:14) ‘Ṣé mo lè rántí àwọn ìgbà kan táwọn ojúgbà mi fẹ́ kí n ṣe ohun tí ò dáa, àmọ́ tí mo kọ̀ láti ṣe ohun tí wọ́n fẹ́? Ṣé àwọn tó máa ràn mí lọ́wọ́ láti ṣe ohun tó tọ́ ni mo yàn lọ́rẹ̀ẹ́?’​—Òwe 13:20.

    Ohun tó lè ràn ẹ́ lọ́wọ́: Wo àpilẹ̀kọ náà “Báwo Ni Mo Ṣe Lè Kọ́ Ẹ̀rí Ọkàn Mi?”

  • Ṣé o mọ̀ pé gbogbo ohun tó o bá ṣe lo máa jíhìn fún Jèhófà?

    Bíbélì sọ pé: “Kálukú wa ló máa jíhìn ara rẹ̀ fún Ọlọ́run”​—Róòmù 14:12.

    Bi ara ẹ pé: ‘Ṣé mi ò kì í tan ara mi jẹ, ṣe mo sì jẹ́ olóòótọ́ nínú àjọṣe mi pẹ̀lú àwọn èèyàn?’ (Hébérù 13:18) ‘Tí mo bá ṣe ohun tí ò dáa, ṣé mo máa ń gbà pé mo jẹ̀bi, ṣé kì í ṣe pé mo máa ń dọ́gbọ́n bo ohun tí mo ṣe mọ́lẹ̀ àbí kí n di ẹ̀bi ẹ̀ ru àwọn ẹlòmíì?’​—Òwe 28:13.

    Ohun tó lè ràn ẹ́ lọ́wọ́: Wo àpilẹ̀kọ náà “Kí Ni Mo Lè Ṣe Nípa Àwọn Àṣìṣe Mi?”

  • Ṣé ò ń ṣe àwọn nǹkan táá jẹ́ kó o túbọ̀ ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Jèhófà?

    Bíbélì sọ pé: “Ẹ sún mọ́ Ọlọ́run, á sì sún mọ́ yín”​—Jémíìsì 4:8

    Bi ara ẹ pé: ‘Kí làwọn nǹkan tí mò ń ṣe kí n lè túbọ̀ ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Jèhófà?’ Bí àpẹẹrẹ, ‘Ṣé mo máa ń ka Bíbélì déédéé?’ (Sáàmù 1:1, 2) ‘Ṣé mo máa ń gbàdúrà déédéé?’ (1 Tẹsalóníkà 5:17) ‘Tí mo bá ń gbàdúrà, ṣé mo máa ń sọ àwọn nǹkan pàtó tí mo fẹ́ kí Jèhófà ṣe fún mi? Ṣé àwọn tó nífẹ̀ẹ́ Jèhófà ni mò ń bá ṣọ̀rẹ́?’​—Sáàmù 15:1, 4.

    Ohun tó lè ràn ẹ́ lọ́wọ́: Wo àpilẹ̀kọ náà “Báwo Ni Bíbélì Ṣe Lè Ràn Mí Lọ́wọ́?​—Apá Kejì: Jẹ́ Kí Bíbélì Gbádùn Mọ́ Ẹ” àti “Kí Nìdí Tó Fi Yẹ Kí N Máa Gbàdúrà?”

ÀBÁ: Tó o bá fẹ́ mọ ohun tó yẹ kó o ṣe láti múra sílẹ̀ fún ìrìbọmi, ka orí 37 nínú ìwé Awọn Ìbéèrè Tí Awọn Ọ̀dọ́ Ń Béèrè​-Awọn Ìdáhùn Tí Ó Gbéṣẹ́, Apá 2. Ní pàtàkì wo àpótí tá a pè ní “Ṣó O Ti Ń Ronú Láti Ṣèrìbọmi?” tó wà lójú ìwé 308 sí 309.

a Kó o lè mọ ohun tó túmọ̀ sí láti ya ara ẹ sí mímọ́ kó o sì ṣèrìbọmi àti ìdí tó fi yẹ kó o ṣe bẹ́ẹ̀, ka àpilẹ̀kọ náà “Ṣé Kí N Ṣèrìbọmi?​—Apá 1.”

Ohun táwọn ojúgbà ẹ sọ

Gabriella.

“Àpótí tá a pè ní ‘Ṣó O Ti Ń Ronú Láti Ṣèrìbọmi?’ tó wà nínú ìwé Àwọn Ọ̀dọ́ Béèrè Pé jẹ́ kí n mọ àwọn àtúnṣe tó yẹ kí n ṣe kí n tó ṣèrìbọmi. Ó tún jẹ́ kí n lè ní àwọn nǹkan pàtó tí mo fẹ́ ṣe nínú ìjọsìn Jèhófà lẹ́yìn tí mo bá ṣèrìbọmi. Ọ̀pọ̀ nǹkan ló máa ní láti ṣe tó o bá ya ara ẹ sí mímọ́, àmọ́ kò sóhun tó dáa tó kéèyàn ya ara ẹ̀ sí mímọ́ fún Jèhófà.”​—Gabriella.

Caleb.

“Nínú Bíbélì, wọ́n sọ fún Tímótì pé: ‘Má ṣe fi àwọn nǹkan tí o ti kọ́ sílẹ̀, tí a sì mú kí o gbà gbọ́.’ ” (2 Tímótì 3:14) “Máa fara balẹ̀ kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì kó lè túbọ̀ dá ẹ lójú pé ohun tó wà nínú ẹ̀ jẹ́ òótọ́. Jèhófà lo fẹ́ yara ẹ̀ sí mímọ́ fún kì í ṣe fáwọn èèyàn, torí náà ohun tí Jèhófà fẹ́ ni kó o jẹ́ kó ṣe pàtàkì jù sí ẹ tó o bá ń ronú pé o fẹ́ ṣèrìbọmi.”​—Caleb.

Àtúnyẹ̀wò: Báwo ni mo ṣe lè múra sílẹ̀ fún ìrìbọmi?

Ṣàyẹ̀wò ohun tó o gbà gbọ́. Ṣé ó dá ẹ lójú pé Ọlọ́run wà àti pé òun ló yẹ kó o máa sìn? Ṣé o gbà pé Jèhófà ló mí sí Bíbélì àti pé ó ní ètò kan tó ń lò láti mú ìfẹ́ rẹ̀ ṣẹ?

Ṣàyẹ̀wò ìwà àti ìṣe ẹ. Ṣé o máa ń fi àwọn ìlànà Jèhófà sílò nígbèésí ayé rẹ? Ṣé o mọ̀ pé gbogbo ohun tó o bá ṣe lo máa jíhìn fún Jèhófà? Ṣé ò ń ṣe àwọn nǹkan táá jẹ́ kó o túbọ̀ ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Jèhófà?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́