Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Dájúdájú, èyí kò túmọ̀ sí pé kò tọ̀nà fún Kristẹni kan láti ṣe àyẹ̀wò láti mọ̀ nípa ìlera ọmọ tí a kò tí ì bí. Àwọn ète ìṣègùn bíi mélòó kan tí Ìwé Mímọ́ fọwọ́ sí lè wà, tí ó lè mú kí oníṣègùn kan dámọ̀ràn irú ipa ọ̀nà bẹ́ẹ̀. Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, àwọn àyẹ̀wò kan lè kan wíwu ọmọ náà léwu, nítorí náà, yóò bọ́gbọ́n mu láti bá dókítà náà sọ̀rọ̀ nípa ìwọ̀nyí. Lẹ́yìn irú àwọn àyẹ̀wò bẹ́ẹ̀, bí a bá rí i pé ọmọ náà ní àwọn àbùkù líle koko, ní àwọn ilẹ̀ kan, àwọn òbí Kristẹni lè wà lábẹ́ ìkìmọ́lẹ̀ láti ṣẹ́yún ọmọ náà. Yóò bọ́gbọ́n mu láti wà ní ìmúrasílẹ̀ láti rọ̀ mọ́ ìlàna Bíbélì.