Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ìtẹ̀jáde Ilé Ìṣọ́, September 1, 1997, ojú ìwé 21 àti 22, sọ pé: “Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà ti ń hára gàgà láti mọ ìgbà ti ọjọ́ Jèhófà yóò dé. Nínú ìháragàgà wọn, wọ́n ti gbìdánwò nígbà míràn láti fojú díwọ̀n ìgbà ti yóò dé. Ṣùgbọ́n nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀, wọ́n ti kùnà, bí àwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù ìjímìjí ti ṣe, láti kọbi ara sí ìkìlọ̀ Ọ̀gá wọn pé a “kò mọ ìgbà tí àkókò tí a yàn kalẹ̀ jẹ́.” (Máàkù 13:32, 33) Àwọn olùyọṣùtì ti fi àwọn Kristẹni olùṣòtítọ́ ṣẹlẹ́yà nítorí tí wọ́n ń retí ohun tí àkókò rẹ̀ kò tí ì tó. (2 Pétérù 3:3, 4) Síbẹ̀síbẹ̀, Pétérù mú un dáni lójú pé, ọjọ́ Jèhófà yóò dé, ní àkókò tí Òún ṣètò pé yóò dé.”