Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Àwọn ènìyàn gbìyànjú láti ti àwọn ìkàléèwọ̀ yìí lẹ́yìn nípa lílọ́ Ìwé Mímọ́ lọ́rùn. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Bíbélì kò sọ ohun tí ó jọ bẹ́ẹ̀, ajẹgàba ẹlẹ́kọ̀ọ́ ìsìn náà, Tertullian, fi kọ́ni pé, nítorí pé obìnrin ló fa “ẹ̀ṣẹ̀ àkọ́kọ́, àti ìtìjú . . . ìparun ayérayé tí ènìyàn wà nínú rẹ̀,” àwọn obìnrin gbọ́dọ̀ máa rìn “kiri bí Éfà, kí wọ́n máa ṣọ̀fọ̀, kí wọ́n sì máa ronú pìwà dà.” Ní gidi, ó rin kinkin mọ́ ọn pé, obìnrin tí ó bá rẹwà lọ́nà àdánidá gbọ́dọ̀ fi ẹwà rẹ̀ pa mọ́ pàápàá.—Fi wé Róòmù 5:12-14; 1 Tímótì 2:13, 14.