Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Fún sáà kan, àwọn Kristẹni tó jẹ́ Júù ní Jerúsálẹ́mù ní ọ̀rúndún kìíní pa oríṣiríṣi ohun tí Òfin Mósè sọ mọ́, bóyá nítorí àwọn ìdí tó tẹ̀ lé e yìí: Àtọ̀dọ̀ Jèhófà ni Òfin náà ti wá. (Róòmù 7:12, 14) Òfin náà ti di àṣà láàárín àwọn Júù. (Ìṣe 21:20) Òfin yìí ni ìjọba ilẹ̀ náà ń lò, tí wọ́n bá sì ta kò ó, ó lè gbé àtakò tí kò nídìí dìde sí iṣẹ́ táwọn Kristẹni ń jẹ́.