Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Àpilẹ̀kọ náà “Àwọn Ọ̀dọ́ Béèrè Pé . . . Báwo Ni Mo Ṣe Lè Sọ Ohun Tó Wà Lọ́kàn Mi fún Un?” (tó wà nínú ìtẹ̀jáde November 8, 2004) ṣàlàyé pé ó lè lòdì sí àṣà wọn láwọn ilẹ̀ kan pé kí obìnrin lọ bá ọkùnrin pé òun fẹ́ káwọn máa fẹ́ra. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé Bíbélì ò lòdì sírú nǹkan bẹ́ẹ̀, ó gba àwọn Kristẹni níyànjú pé kí wọ́n má ṣe ohun tó bá lè mú ẹlòmíì kọsẹ̀. Nítorí náà, ó yẹ káwọn tó bá fẹ́ rí ìbùkún Ọlọ́run tẹ̀ lé ìmọ̀ràn inú Bíbélì yìí kí wọ́n tó lọ dẹnu kọ ọkùnrin.—Mátíù 18:6; Róòmù 14:13; 1 Kọ́ríńtì 8:13.