Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Kí ọkùnrin tàbí obìnrin àgbàlagbà máa lo ọmọdé láti fi tẹ́ ìfẹ́ ara rẹ̀ fún ìbálòpọ̀ lọ́rùn ló ń jẹ́ bíbá ọmọdé ṣèṣekúṣe. Lára àṣà yìí náà ni ohun tí Bíbélì pè ní àgbèrè, tàbí por·neiʹa wà. Lára àwọn nǹkan tó túmọ̀ sí por·neiʹa ni fífọwọ́ pa ẹ̀yà ìbálòpọ̀, bíbáni lò pọ̀, fífi ẹnu pọ́n ẹ̀yà ìbálòpọ̀ lá, tàbí kí ọkùnrin máa ki nǹkan ọmọkùnrin rẹ̀ bọnú ihò ìdí obìnrin tàbí ọkùnrin bíi tiẹ̀. Àwọn nǹkan míì tó jẹ mọ́ ìṣekúṣe, bíi fífọwọ́ pani lọ́yàn, fífi ìṣekúṣe lọni, fífi àwòrán oníhòòhò han ọmọdé, yíyọjú wo ẹni tó bọ́ra sílẹ̀ tàbí yíyọjú wo àwọn tó ń bára wọn lò pọ̀ àti ṣíṣí ara sílẹ̀ níbi tí kò yẹ, lè já sí ohun tí Bíbélì dẹ́bi fún tó sì pè ní “ìwà àìníjàánu” tàbí fífi “ìwà ìwọra hu onírúurú ìwà àìmọ́ gbogbo.”—Gálátíà 5:19-21; Éfésù 4:19.