Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
e Níbòmíì tá a tún ti lo ọ̀rọ̀ náà “ọ̀run” lọ́nà yìí, ìyẹn nínú àsọtẹ́lẹ̀ “ọ̀run tuntun” nínú ìwé Aísáyà 65:17, 18, ó kọ́kọ́ ní ìmúṣẹ lórí ètò ìjọba tuntun tó kan Gómìnà Serubábélì àti Àlùfáà Àgbà Jéṣúà. Lẹ́yìn táwọn Júù padà láti ìgbèkùn Bábílónì ni ìjọba tuntun náà fìdí múlẹ̀ ní Ilẹ̀ Ìlérí.—2 Kíróníkà 36:23; Ẹ́sírà 5:1, 2; Aísáyà 44:28.