Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
f Nígbà yẹn, àwọn Akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì ò tíì mọ̀ pé kò sí àlàfo ọdún kankan láàárín sànmánì “ṣáájú Ìbí Kristi” àti sànmánì “Lẹ́yìn Ikú Olúwa Wa,” àmọ́, ó bà ni, kò bà jẹ́. Nígbà tí ìwádìí mú kó pọn dandan fún wọn láti ṣàtúnṣe ọdún 606 ṣáájú Ìbí Kristi sí ọdún 607 ṣááju Sànmánì Kristẹni, wọ́n yọ àlàfo ọdún kan yẹn kúrò, tí ìsọtẹ́lẹ̀ náà fi wá já sí òótọ́ ní ọdún “1914 Lẹ́yìn Ikú Olúwa Wa.”—Wo ojú ìwé 203 sí 204 nínú ìwé “Otitọ Yio Sọ Nyin Di Ominira,” tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà tẹ̀ jáde lédè Yorùbá lọ́dún 1948.