Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ìràwọ̀ méje náà tó wà ní ọwọ́ ọ̀tún Jésù dúró fún àwọn alábòójútó ẹni àmì òróró nínú ìjọ Kristẹni, àwọn alàgbà inú èyí tó pọ̀ jù lọ lára iye tó lé ní ọ̀kẹ́ márùn-ún [100,000] ìjọ tó wà láyé báyìí jẹ́ ara ogunlọ́gọ̀ ńlá náà. (Ìṣípayá 1:16; 7:9) Ipò wo ni wọ́n wà? Níwọ̀n bó ti jẹ́ pé ẹ̀mí mímọ́ la fi yàn wọ́n sípò nípasẹ̀ ẹgbẹ́ ẹrú olóòótọ́ àti olóye tí wọ́n jẹ́ ẹni àmì òróró, a lè sọ pé àwọn wọ̀nyí wà ní ọwọ́ ọ̀tun Jésù níbi tó ti ń ṣàkóso wọn, nítorí olùṣọ́ àgùntàn tó ń sìn lábẹ́ rẹ̀ làwọn náà. (Aísáyà 61:5, 6; Ìṣe 20:28) Wọ́n ń ṣètìlẹ́yìn fún “àwọn ìràwọ̀ méje” ní ti pé wọ́n ń sìn níbi táwọn arákùnrin ẹni àmì òróró tó kúnjú ìwọ̀n ò bá ti sí.