Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
d Ọ̀rọ̀ Gíríìkì tá a lò níhìn-ín wá láti inú ọ̀rọ̀ náà ba·sa·niʹzo, èyí tá a máa ń lò nígbà mìíràn fún ìdálóró gidi. Ṣùgbọ́n, a tún lè lò ó fún ohun tó ń da èèyàn lọ́kàn rú bíi pé ó ń dá a lóró. Bí àpẹẹrẹ, ní 2 Pétérù 2:8, a kà pé Lọ́ọ̀tì “ń mú ọkàn òdodo rẹ̀ joró” nítorí ìwà ibi tó rí ní Sódómù. Àwọn aṣáájú ìsìn ayé ìgbà àwọn àpọ́sítélì fara gbá irú ìdálóró ọkàn bẹ́ẹ̀ bó tilẹ̀ jẹ́ pé, ó dájú pé, nǹkan míì tó yàtọ̀ pátápátá ló fà á.