Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Àwọn ọ̀mọ̀wé sọ pé ìjọsìn ni ẹ̀mí orílẹ̀-èdè tèmi lọ̀gá já sí. Fún ìdí yìí, ńṣe làwọn èèyàn tí wọ́n jẹ́ onífẹ̀ẹ́ orílẹ̀-èdè ẹni ń jọ́sìn apá tí orílẹ̀-èdè tí wọ́n ń gbé ń ṣojú fún lára ẹranko ẹhànnà náà. Ohun kan rèé tẹ́nì kan kọ nípa ìfẹ́ orílẹ̀-èdè ẹni lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà, ó ní: “Ìfẹ́ orílẹ̀-èdè ẹni, tí a wò gẹ́gẹ́ bí ìjọsìn, kò yàtọ̀ sí àwọn ètò ìsìn ńlá ti ìgbà àtijọ́ . . . Ńṣe làwọn tó nífẹ̀ẹ́ orílẹ̀-èdè wọn ju tàwọn mìíràn lọ ka orílẹ̀-èdè wọn sí ọlọ́run wọn, òun ni wọ́n sì gbára lé. Wọ́n gbà pé òun ló lágbára láti ràn wọ́n lọ́wọ́. Wọ́n sì tún gbà pé òun ló lè fún àwọn ní ìjẹ́pípé àti ayọ̀. Òun ni wọ́n ń tẹrí ba fún tó bá di ti ọ̀ràn ìsìn. . . . Wọ́n gbà pé orílẹ̀-èdè àwọn máa wá títí gbére, àti pé ńṣe ni ikú àwọn ọmọ rẹ̀ adúróṣinṣin wúlẹ̀ ń fi kún òkìkí àti ògo rẹ̀ tí kì í pa rẹ́.”—Ọ̀rọ̀ Carlton J. F. Hayes tí wọ́n fà yọ ní ojú ìwé 359 ìwé náà, What Americans Believe and How They Worship, látọwọ́ J. Paul Williams.