Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a kò dárúkọ áńgẹ́lì yìí, ó dà bí pé òun kan náà ni ẹni tí a gbọ́ ohùn rẹ̀ tí ó ń sọ fún Gébúrẹ́lì pé kí ó ran Dáníẹ́lì lọ́wọ́ nípa ìran tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ rí nígbà yẹn. (Fi Dáníẹ́lì 8:2, 15, 16 wé Da 12:7, 8.) Síwájú sí i, Dáníẹ́lì 10:13 fi hàn pé Máíkẹ́lì, “ọ̀kan nínú àwọn ọmọ aládé tí ó wà ní ipò iwájú pátápátá,” wá ran áńgẹ́lì yìí lọ́wọ́. Nípa báyìí, áńgẹ́lì tí a kò dárúkọ rẹ̀ yìí ti ní àǹfààní láti bá Gébúrẹ́lì àti Máíkẹ́lì ṣiṣẹ́ pọ̀ tímọ́tímọ́.