Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Ọ̀rọ̀ Hébérù yẹn tan mọ́ “òkúta,” níwọ̀n bí a ti ń fi àwọn òkúta kéékèèké ṣẹ́ kèké. Nígbà mìíràn a máa ń lo ọ̀nà yìí láti fi pín ilẹ̀. (Númérì 26:55, 56) Ìwé Handbook on the Book of Daniel sọ pé níhìn-ín, ọ̀rọ̀ náà túmọ̀ sí “ohun tí (Ọlọ́run) yàn sọ́tọ̀ fún ẹnì kan.”