Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Orúkọ àwọn ará Mídíà nìkan ni Aísáyà mẹ́nu kàn, àmọ́ orílẹ̀-èdè bíi mélòó kan ni yóò para pọ̀ gbógun ti Bábílónì, àwọn ni, Mídíà, Páṣíà, Élámù, àti àwọn orílẹ̀-èdè kéékèèké mìíràn. (Jeremáyà 50:9; 51:24, 27, 28) Àwọn ará Mídíà pa pọ̀ mọ́ Páṣíà làwọn orílẹ̀-èdè àgbègbè ibẹ̀ máa ń pè ní “ará Mídíà.” Àti pé, nígbà ayé Aísáyà, Mídíà lorílẹ̀-èdè tó gba iwájú. Ìgbà tí Kírúsì di olórí ni Páṣíà ṣẹ̀ṣẹ̀ gba iwájú.