Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Nígbà mìíràn, wọ́n máa ń pe Kírúsì ọba Páṣíà ní “Ọba Áńṣánì,” àgbègbè tàbí ìlú kan ní Élámù sì ni Áńṣánì yìí. Nígbà ayé Aísáyà—ọ̀rúndún kẹjọ ṣááju Sànmánì Tiwa—ó ṣeé ṣe kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì má mọ̀ nípa Páṣíà, àmọ́ ṣá, wọ́n á mọ Élámù. Ìyẹn lè jẹ́ ìdí tí Aísáyà fi dárúkọ Élámù níhìn-ín dípò Páṣíà.