Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Àsọtẹ́lẹ̀ yìí ti ní ìmúṣẹ nígbà tó fi máa di ìgbà ayé Málákì. (Málákì 1:3) Málákì ròyìn pé àwọn ọmọ Édómù retí àtitún ilẹ̀ wọn tó ti dahoro kọ́. (Málákì 1:4) Àmọ́ o, ìfẹ́ Jèhófà kọ́ nìyẹn, nígbà tó sì ṣe, àwọn ará ibòmíràn, ìyẹn àwọn Nábátíà, wá ń gbé ibi tó jẹ́ ilẹ̀ Édómù tẹ́lẹ̀ rí.