Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Lẹ́yìn tí Senakéríbù ṣubú, àwọn orílẹ̀-èdè àgbègbè ibẹ̀ wá kó wúrà, fàdákà, àtàwọn ohun iyebíye mìíràn wá fún Hesekáyà. Nínú 2 Kíróníkà 32:22, 23, 27, a kà á pé, “Hesekáyà sì wá ní ọrọ̀ àti ògo ní iye púpọ̀ gan-an” àti pé “ó sì wá di ẹni tí a gbé ga ní ojú gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.” Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ẹ̀bùn wọ̀nyí ló jẹ́ kí ó rí ìṣúra tò padà sí ilé ìṣúra rẹ̀ tó ti gbọ́n gbẹ nígbà tó san owó òde fún àwọn ará Ásíríà.