Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ó jọ pé ibi táa mọ̀ sí Sípéènì nísinsìnyí ni Táṣíṣì wà láyé ìgbà yẹn. Àmọ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn ìwé kan ṣe wí, wọ́n ní irú àwọn ọkọ̀ òkun kan, ìyẹn “àwọn ọkọ̀ onígbòkun ńlá tó ń rìn lójú agbami òkun,” tó jẹ́ pé irú wọn ló “kúnjú òṣùwọ̀n láti máa wá sí Táṣíṣì,” ni gbólóhùn náà, “ọkọ̀ òkun Táṣíṣì” ń tọ́ka sí, ìyẹn ni pé, ó tọ́ka sí àwọn ọkọ̀ òkun tó ṣeé lò fún ìrìn àjò ọ̀nà jíjìn lọ sí àwọn èbúté ti ilẹ̀ òkèèrè.—1 Àwọn Ọba 22:48.