Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Nígbà tí Jeremáyà 52:15 ń sọ nípa bí nǹkan ṣe rí lẹ́yìn tí Jerúsálẹ́mù ṣubú sọ́wọ́ àwọn ará Bábílónì tán, ó mẹ́nu kan “àwọn kan lára àwọn ẹni rírẹlẹ̀ nínú àwọn ènìyàn náà àti ìyókù àwọn ènìyàn tí a fi sílẹ̀ sí ìlú ńlá náà.” Ìwé gbédègbẹ́yọ̀ náà, Insight on the Scriptures, Apá kìíní, ojú ewé 415, sọ pé: “Gbólóhùn náà, ‘tí a fi sílẹ̀ sí ìlú ńlá náà’ ń fi hàn dájúdájú pé àwọn tó pọ̀ gan-an ló ti tipa ìyàn, àrùn, tàbí iná kú, tàbí kí wọ́n ti bá ogun lọ.”