Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Nígbà tí Jèhófà ń sọ̀rọ̀ nípa Jóòbù, ó sọ pé: “Kò sí ẹni tó dà bí rẹ̀ ní ayé.” (Jóòbù 1:8) Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ẹ̀yìn ìgbà tí Jósẹ́fù kú ni Jóòbù gbé ayé, ó sì jọ pé Ọlọ́run ò tíì yan Mósè ṣe aṣáájú Ísírẹ́lì nígbà yẹn. Torí náà, ó bọ́gbọ́n mu láti gbà pé kò sí ẹnì kankan láyé nígbà yẹn tó jẹ́ olóòótọ́ bíi ti Jóòbù.