Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Kí Jésù tó lè san ìràpadà tó ṣe rẹ́gí pẹ̀lú ohun tí Ádámù sọ nù, ó gbọ́dọ̀ jẹ́ ẹni pípé tó ti dàgbà nígbà tó bá máa kú, kì í ṣe ọmọ kékeré. Rántí pé ṣe ni Ádámù mọ̀ọ́mọ̀ dẹ́ṣẹ̀, ó mọ̀ pé ohun tóun ṣe ò dáa àti pé Jèhófà máa fìyà jẹ òun tóun bá ṣe é. Torí náà, kí Jésù tó lè di “Ádámù ìkẹyìn” kó sì bo ẹ̀ṣẹ̀ náà mọ́lẹ̀, ó ti ní láti dàgbà torí ìyẹn lá jẹ́ kó mọ ohun tó ń ṣe, kó sì pinnu pé òun máa jẹ́ adúróṣinṣin sí Jèhófà. (1 Kọ́ríńtì 15:45, 47) Nípa bẹ́ẹ̀, bí Jésù ṣe jẹ́ olóòótọ́ sí Jèhófà jálẹ̀ ìgbésí ayé ẹ̀ àti bó ṣe kú torí àwa èèyàn jẹ́ “ìwà òdodo kan.”—Róòmù 5:18, 19.