Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ní 2 Tímótì 4:2, Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run sọ pé nígbà míì ó lè pọn dandan káwọn alàgbà “báni wí,” kí wọ́n “fi ìbáwí tọ́ni sọ́nà,” kí wọ́n sì “gbani níyànjú.” Ọ̀rọ̀ Gíríìkì tá a túmọ̀ sí “gbani níyànjú” (pa·ra·ka·leʹo) tún lè túmọ̀ sí “láti fúnni ní ìṣírí.” Ọ̀rọ̀ Gíríìkì míì tó jọ ọ́ ni pa·raʹkle·tos, ó sì lè tọ́ka sí agbẹjọ́rò tó máa ń ran àwọn èèyàn lọ́wọ́ nílé ẹjọ́. Torí náà, tẹ́nì kan bá tiẹ̀ ṣe ohun tí kò dáa, tó wá gba pé káwọn alàgbà bá a wí, wọ́n máa ń fi sọ́kàn pé ṣe ni wọ́n fẹ́ ran ẹni náà lọ́wọ́ kó lè pa dà ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú Jèhófà.