Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Láti ọdún 455 Ṣ.S.K. sí ọdún 1 Ṣ.S.K., iye ọdún tó wà ńbẹ̀ jẹ́ Ọgọ́rùn-ún mẹ́rin ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta [454] ọdún. Ọdún kan ló wà láàárín ọdún 1 Ṣ.S.K. sí ọdún 1 S.K. (nítorí pé òǹkà kò bẹ̀rẹ̀ látorí òdo, orí oókan ló ti bẹ̀rẹ̀). Ọdún méjìdínlọ́gbọ̀n ló sì wà láàárín ọdún 1 S.K. sí ọdún 29 S.K. Tá a bá ro mẹ́tẹ̀ẹ̀ta yìí pọ̀, yóò fún wa ní ọgọ́rùn-ún mẹ́rin ó lé ọgọ́rin àti mẹ́ta [483] ọdún. Àárín ọ̀sẹ̀ ọdún àádọ́rin ni wọ́n ‘ké Jésù kúrò’ tàbí tí wọ́n pa á, ìyẹn sì jẹ́ ní ọdún 33 S.K. (Dáníẹ́lì 9:24, 26) Ka orí kọkànlá ìwé Kíyè sí Àsọtẹ́lẹ̀ Dáníẹ́lì! àti Insight on the Scriptures, Ìdìpọ̀ Kejì, ojú ìwé 899 sí 901. Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà la ṣe ìwé méjèèjì.