Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ìlú Kálà (ìyẹn Nímírúdù) tí Aṣunásípà tún kọ́ jẹ́ nǹkan bíi kìlómítà márùndínlógójì sí àríwá ìlà oòrùn Nínéfè. Àwọn àwòrán ara ògiri tí wọ́n rí ní Kálà wà ní Ibi Ìkóhun-Ìṣẹ̀ǹbáyé-Sí Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì. Ohun tá a rí kà nípa àwọn àwòrán ara ògiri náà ni pé: “Aṣunásípà sọ gbogbo ìwà òǹrorò àti ìwà ìkà tó burú jáì tó fi máa ń gbógun lọ bá àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn. Ní àwọn ìlú tí wọ́n bá sàga tì, wọ́n máa ń so àwọn tí wọ́n bá mú lóǹdè rọ̀ sórí òpó igi tàbí kí wọ́n kàn wọ́n mọ́ òpó igi . . . ; wọ́n máa ń bó awọ ara àwọn ọ̀dọ́kùnrin àtàwọn ọ̀dọ́bìnrin lóòyẹ̀.”—Archaeology of the Bible.