Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé àsọtẹ́lẹ̀ yìí ní ìmúṣẹ rẹ̀ àkọ́kọ́ lákòókò àwọn Mákábì. Nígbà yẹn, àwọn Júù lábẹ́ àwọn Mákábì lé àwọn ọ̀tá wọn kúrò ní Júdà wọ́n sì tún tẹ́ńpìlì yà sí mímọ́. Ìyẹn ló mú kó ṣeé ṣe fún àṣẹ́kù àwọn Júù láti kí Mèsáyà káàbọ̀ nígbà tó fara hàn.—Dáníẹ́lì 9:25; Lúùkù 3:15-22.