Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Àwọn kan lára àwọn baba ńlá tó jẹ́ olùṣòtítọ́ ní ju ìyàwó kan lọ. Lásìkò tí Jèhófà bá àwọn àtàwọn ọmọ Ísírẹ́lì tara lò, ó fàyè gbà wọ́n láti ní ju aya kan lọ. Òun kọ́ ló dáa sílẹ̀, àmọ́ kò jẹ́ kí wọ́n ki àṣejù bọ̀ ọ́. Àmọ́ ṣá o, àwọn Kristẹni máa ń fi sọ́kàn pé Jèhófà kò fàyè gba àṣà kíkó obìnrin jọ mọ́ láàárín àwọn èèyàn rẹ̀.—Mátíù 19:9; 1 Tímótì 3:2.