Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
e Àwọn kan sọ pé ìṣẹ̀lẹ̀ yìí ni Pọ́ọ̀lù ń tọ́ka sí nígbà tó sọ fáwọn ará Kọ́ríńtì pé “a ò . . . mọ̀ pé ẹ̀mí wa ò ní bọ́.” (2 Kọ́r. 1:8) Àmọ́, ó lè jẹ́ ìṣẹ̀lẹ̀ kan tó burú jùyẹn lọ ló ní lọ́kàn. Nígbà tí Pọ́ọ̀lù kọ̀wé pé òun “bá àwọn ẹranko jà ní Éfésù,” ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ìgbà tó kojú àwọn ẹranko ẹhànnà ní gbọ̀ngàn ìwòran ló ń sọ tàbí báwọn èèyàn ṣe ṣenúnibíni sí i. (1 Kọ́r. 15:32) Àlàyé méjèèjì yìí ló bá ohun tí Pọ́ọ̀lù sọ mu.