Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
f Yíya ẹja àtàtà àti èyí tí kò yẹ sọ́tọ̀ yàtọ̀ sí yíya àgùntàn àti ewúrẹ́ sọ́tọ̀. (Mát. 25:31-46) Ìyàsọ́tọ̀ tàbí ìdájọ́ ìkẹyìn ti àgùntàn àti ewúrẹ́ yóò wáyé nígbà ìpọ́njú ńlá tó ń bọ̀. Títí di ìgbà yẹn, àwọn tó dà bí ẹja tí kò yẹ ṣì lè pa dà sọ́dọ̀ Jèhófà kí a sì kó wọn jọ sínú ìjọ Ọlọ́run.—Mál. 3:7.