Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ìwé kan tó dá lórí Bíbélì sọ nípa àwọn ọ̀rọ̀ Sátánì yìí pé: “Bó ṣe rí nígbà ìdẹwò àkọ́kọ́, tí Ádámù àti Éfà kó sọ́wọ́ Sátánì . . . , ọ̀rọ̀ yìí dá lórí ṣíṣe ìfẹ́ Sátánì tàbí ìfẹ́ Ọlọ́run, wọ́n sì ní láti pinnu ẹni tí wọ́n máa jọ́sìn nínú àwọn méjèèjì. Ṣe ni Sátánì ń gbéra ga, tó sì ń fi ara rẹ̀ ṣe ọlọ́run dípò Ọlọ́run kan ṣoṣo náà.”