Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé kò pẹ́ sígbà tí Ọlọ́run lé Ádámù àti Éfà kúrò ní Édẹ́nì ni wọ́n lóyún Ébẹ́lì. (Jẹ́n. 4:1, 2) Jẹ́nẹ́sísì 4:25 sọ pé Ọlọrun yan Sẹ́ẹ̀tì “rọ́pò Ébẹ́lì.” Ẹni àádóje (130) ọdún ni Ádámù nígbà tó bí Sẹ́ẹ̀tì, lẹ́yìn tí Kéènì pa Ébẹ́lì nípakúpa. (Jẹ́n. 5:3) Torí náà, ó ṣeé ṣe kí Ébẹ́lì jẹ́ ẹni nǹkan bí ọgọ́rùn-ún (100) ọdún nígbà tí Kéènì pa á.