Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Èyí tó pọ̀ jù nínú àwọn Júù tó wà nígbèkùn ló ń gbé níbi tí kò fi bẹ́ẹ̀ jìnnà sí Bábílónì. Bí àpẹẹrẹ, Ìsíkíẹ́lì wà lára àwọn Júù tó ń gbé nítòsí odò Kébárì. (Ìsík. 3:15) Àmọ́, àwọn Júù mélòó kan wà tó jẹ́ pé inú ìlú yẹn gangan ni wọ́n wà. Lára àwọn tó wà níbẹ̀ ni “àwọn ọmọ ọba àti ọmọ àwọn èèyàn pàtàkì.”—Dán. 1:3, 6; 2 Ọba 24:15.