Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ní nǹkan bí ọdún 760 C.E., àwùjọ àwọn Júù kan tí a mọ̀ sí àwọn Karaite fi dandangbọ̀n béèrè fún títúbọ̀ tòròpinpin mọ́ Ìwé Mímọ́. Nítorí pé wọ́n kọ ọláàṣẹ àwọn rabbi, “Òfin Ọlọ́rọ̀-Ẹnu,” àti Talmud, wọ́n ní ìdí púpọ̀ síi láti dáàbòbo àwọn ẹsẹ̀ Bibeli ní ṣísẹ̀ntẹ̀lé. Àwọn ìdílé kan láti inú ẹgbẹ́ àwùjọ yìí di awọn Masorete ògbógi adàwékọ.