Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Jálẹ̀ Ìwé Mímọ́ Lédè Heberu, àwọn ọkùnrin àti obìnrin tí wọ́n ti lọ́kọ tí wọ́n sì ti láya ni a tọ́ka sí ní ọ̀pọ̀ ìgbà gẹ́gẹ́ bí “ọkọ” (Heberu, ʼish) àti “aya” (Heberu, ʼish·shahʹ). Fún àpẹẹrẹ, ní Edeni, ọ̀rọ̀ náà tí Jehofa lò, kì í ṣe “olówó” àti ‘ẹni tí a ni,’ ṣùgbọ́n “ọkọ” àti “aya.” (Genesisi 2:24; 3:16, 17) Àsọtẹ́lẹ̀ Hosea sọ pé lẹ́yìn pípadà dé láti oko-òǹdè, Israeli yóò fi ìrònúpìwàdà pe Jehofa ní “Ọkọ mi,” kì í sì ṣe “Olówó mi” mọ́. Èyí lè dámọ̀ràn pé ọ̀rọ̀ náà “ọkọ” ní ìgbéyọsọ́kàn oníjẹ̀lẹ́ńkẹ́ ju “olówó” lọ.—Hosea 2:16, NW.