Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Ẹgbẹ́ wọ́n ya láti inú ẹgbẹ́ Hásídì, ẹgbẹ́ kan tí ó dìde ní àwọn ọ̀rúndún ṣáájú láti ṣẹ́pá agbára ìdarí Gíríìkì. Àwọn Hásídì mú orúkọ wọn láti inú ọ̀rọ̀ Hébérù náà chasi·dhimʹ, tí ó túmọ̀ sí “àwọn ẹni ìdúróṣinṣin” tàbí “àwọn onítara ìsìn.” Bóyá wọ́n rò pé àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tí ó mẹ́nu kan “àwọn ẹni ìdúróṣinṣin” Jèhófà tọ́ka sí wọn lọ́nà àrà ọ̀tọ̀. (Orin Dáfídì 50:5) Àwọn, pẹ̀lú àwọn Farisí tí ó dìde lẹ́yìn wọn, jẹ́ agbawèrèmẹ́sìn, àwọn tí wọ́n yan ara wọn sípò olùgbèjà ọ̀rọ̀ Òfin.