Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ní ṣíṣàgbéyẹ̀wò ohun tí Òfin Mósè ti gbé kalẹ̀, àwọn kan ti béèrè bí Bánábà, ọmọ Léfì kan, ṣe wá di ẹni tí ó ní ilẹ̀. (Númérì 18:20) Ṣùgbọ́n, ó yẹ kí a kíyè sí i pé, kò ṣe kedere bóyá Palẹ́sìnì ni ilẹ̀ náà wà tàbí Kípírọ́sì. Síwájú si, ó ṣeé ṣe kí èyí wulẹ̀ jẹ́ ilẹ̀ ìsìnkú tí Bánábà ti rà ní àgbègbè Jerúsálẹ́mù. Ohun yòówù tí ì báà jẹ́, Bánábà ta ilẹ̀ rẹ̀ láti ṣèrànwọ́ fún àwọn ẹlòmíràn.