Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
f Nínú òwe àgùntàn àti ewúrẹ́, Ọmọ ènìyàn dé nínú ògo rẹ̀ nígbà ìpọ́njú ńlá, ó sì jókòó láti máa ṣèdájọ́. Ó ṣèdájọ́ àwọn èèyàn lórí bóyá wọ́n kọ́wọ́ ti àwọn ẹni àmì òróró arákùnrin Kristi lẹ́yìn tàbí wọn kò ṣe bẹ́ẹ̀. Bó bá lọ jẹ́ pé gbogbo àwọn arákùnrin Kristi yóò ti kúró lórí ilẹ̀ ayé tipẹ́tipẹ́ kó tó wá ṣèdájọ́, ìlànà tó fẹ́ fi ṣèdájọ́ yìí kò ní nítumọ̀ mọ́.—Mátíù 25:31-46.