Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ohun ìríra ni nǹkan wọ̀nyí jẹ́ sí Jèhófà fúnra rẹ̀. Fún àpẹẹrẹ, Éfésù 4:29 pe ọ̀rọ̀ ìríra ní “àsọjáde jíjẹrà.” Ọ̀rọ̀ Gíríìkì tá a lò fún “jíjẹrà” ń tọ́ka ní tààràtà sí èso, ẹja, tàbí ẹran tó ti rà. Irú ọ̀rọ̀ bẹ́ẹ̀ ń ṣàgbéyọ bí ọ̀rọ̀ èébú tàbí ọ̀rọ̀ àlùfààṣá ṣe gbọ́dọ̀ kó wa nírìíra. Bákan náà, a sábà máa ń pe àwọn òrìṣà ní “ẹlẹ́bọ́tọ” nínú Ìwé Mímọ́. (Diutarónómì 29:17; Ìsíkíẹ́lì 6:9) Bá a ṣe máa ń sá fún ẹlẹ́bọ́tọ, tàbí ìgbẹ́, ràn wá lọ́wọ́ láti lóye bí irú ìbọ̀rìṣà èyíkéyìí ṣe máa kó Ọlọ́run nírìíra tó.