Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ọdún 61 Sànmánì Tiwa ló kọ lẹ́tà náà sáwọn Hébérù. Tó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀, nǹkan bí ọdún márùn-ún péré lẹ́yìn náà ni ẹgbẹ́ ọmọ ogun Cestius Gallus yí Jerúsálẹ́mù ká. Kò sì pẹ́ tí ẹgbẹ́ ọmọ ogun ọ̀hún fi káńgárá wọn, táwọn Kristẹni tó wà lójúfò fi lè sá lọ. Ọdún mẹ́rin lẹ́yìn ìyẹn ni ẹgbẹ́ ọmọ ogun Róòmù lábẹ́ Ọ̀gágun Titus wá pa ìlú ńlá náà run.