a Ọ̀rọ̀ Gíríìkì kan náà tí Pọ́ọ̀lù lò fún “ìmúlẹ̀mófo” ni wọ́n lò nínú Bíbélì Gíríìkì ti ìtumọ̀ Septuagint láti fi túmọ̀ ọ̀rọ̀ kan tí Sólómọ́nì lò léraléra nínú ìwé Oníwàásù, ọ̀rọ̀ náà sì ni “asán ni gbogbo rẹ̀!”—Oníwàásù 1:2, 14; 2:11, 17; 3:19; 12:8.