Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Bíbélì kò sọ ohun tí ‘ẹ̀gún inú ẹran ara’ Pọ́ọ̀lù jẹ́ gan-gan. Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ àìlera ara kan ni, irú bí àìsàn ojú. Gbólóhùn náà, ‘ẹ̀gún nínú ẹran ara’ sì tún lè tọ́ka sáwọn èké àpọ́sítélì àtàwọn mìíràn tí wọn ò fara mọ́ jíjẹ́ tí Pọ́ọ̀lù jẹ́ àpọ́sítélì, tínú wọn ò sì dùn sí iṣẹ́ òjíṣẹ́ tó ń ṣe.—2 Kọ́ríńtì 11:6, 13-15; Gálátíà 4:15; 6:11.