Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Àwọn ọ̀mọ̀wé kan sọ pé ohun tí àpèjúwe náà dá lé lórí tiẹ̀ lè nítumọ̀ mìíràn tó ju pé ẹyẹ ológoṣẹ́ náà kú nígbà tó jábọ́ lulẹ̀. Wọ́n ni ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé bí ẹyẹ náà ṣe máa ń fò wálẹ̀ láti jẹun ni ọ̀rọ̀ ìpilẹ̀ṣẹ̀ tí wọ́n lò fún gbólóhùn yìí ń tọ́ka sí. Bó bá jẹ́ bẹ́ẹ̀ lọ̀rọ̀ rí, a jẹ́ pé Ọlọ́run ń kíyè sí ẹyẹ yìí ó sì ń bójú tó o lójoojúmọ́, kì í ṣe pé ó ń mọ̀ nígbà tó bá kú nìkan.—Mátíù 6:26.