Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Owó ìràpadà tí Ọlọ́run san yìí ni ìwàláàyè ènìyàn pípé nítorí ohun tí Ádámù sọ nù nìyẹn. Gbogbo ìran èèyàn ló ti di ẹlẹ́sẹ̀, nítorí náà kò sí ẹ̀dá èèyàn àláìpé kankan tó lè rà wá padà. Ìdí rèé tí Ọlọ́run fi rán Ọmọ rẹ̀ wá láti ọ̀run pé kó wá rà wá padà. (Sáàmù 49:7-9) Tó o bá fẹ́ àlàyé síwájú sí i lórí kókó yìí, wo orí keje nínú ìwé Ìmọ̀ Tí Ń Sinni Lọ sí Ìyè Àìnípẹ̀kun tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe.