Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Onírúurú ọ̀nà la lè gbà túmọ̀ ọ̀rọ̀ Gíríìkì tí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù lò, èyí tá a tú sí ìfòyebánilò nínú ẹsẹ Bíbélì yẹn. Ìwé kan tá a ṣèwádìí nínú rẹ̀ sọ pé: “Lára ohun tí ọ̀rọ̀ Gíríìkì náà túmọ̀ sí ni kéèyàn yááfì ohun tó jẹ́ ẹ̀tọ́ rẹ̀, kéèyàn máa gba tàwọn ẹlòmíì rò, kéèyàn jẹ́ oníwà pẹ̀lẹ́.” Ọ̀rọ̀ yìí tún kan kéèyàn jẹ́ afòyebánilò, ẹni tó lè juwọ́ sílẹ̀ tí kì í sì í rin kinkin mọ́ òfin tàbí ẹ̀tọ́ rẹ̀.